1 Kronika 1:1-54 OYCB
[1] Adamu, Seti, Enoṣi, [2] Kenani, Mahalaleli, Jaredi, [3] Enoku, Metusela, Lameki, Noa. [4] Àwọn ọmọ Noa: Ṣemu, Hamu àti Jafeti. [5] Àwọn ọmọ Jafeti ni: Gomeri, Magogu, Madai; Jafani, Tubali, Meṣeki àti Tirasi. [6] Àwọn ọmọ Gomeri ni: Aṣkenasi, Rifati àti Togarma. [7] Àwọn ọmọ Jafani ni: Eliṣa, Tarṣiṣi, Kittimu, àti Dodanimu. [8] Àwọn ọmọ Hamu ni: Kuṣi, Ejibiti, Puti, àti Kenaani. [9] Àwọn ọmọ Kuṣi ni: Seba, Hafila, Sabta, Raama, àti Sabteka. Àwọn ọmọ Raama: Ṣeba àti Dedani. [10] Kuṣi sì bí Nimrodu ẹni tí ó di alágbára jagunjagun ní ayé. [11] Ejibiti sì bí Ludimu, Anamimu, Lehabimu, Naftuhimu, [12] Patrusimu, Kasluhimu (láti ọ̀dọ̀ ẹni tí àwọn ará Filistini ti wá) àti àwọn ará Kaftorimu. [13] Kenaani sì bí Sidoni àkọ́bí rẹ̀, àti Heti, [14] àti àwọn ará Jebusi, àti àwọn ará Amori, àti àwọn ará Girgaṣi, [15] àti àwọn ará Hifi, àti àwọn ará Arki, àti àwọn ará Sini, [16] àti àwọn ará Arfadi, àti àwọn ará Semari, àti àwọn ará Hamati. [17] Àwọn ọmọ Ṣemu ni: Elamu, Aṣuri, Arfakṣadi, Ludi àti Aramu. Àwọn ọmọ Aramu: Usi, Huli, Geteri, àti Meṣeki. [18] Arfakṣadi sì bí Ṣela, Ṣela sì bí Eberi. [19] Eberi sì bí ọmọ méjì: ọ̀kan ń jẹ́ Pelegi, nítorí ní ìgbà ọjọ́ rẹ̀ ni ilẹ̀ ya; orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Joktani. [20] Joktani sì bí Almodadi, Ṣelefi, Hasarmafeti, Jera. [21] Hadoramu, Usali, Dikla, [22] Ebali, Abimaeli, Ṣeba. [23] Ofiri, Hafila, àti Jobabu. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Joktani. [24] Ṣemu, Arfakṣadi, Ṣela, [25] Eberi, Pelegi. Reu, [26] Serugu, Nahori, Tẹra, [27] àti Abramu (tí ń ṣe Abrahamu). [28] Àwọn ọmọ Abrahamu: Isaaki àti Iṣmaeli. [29] Èyí ni àwọn ọmọ náà: Nebaioti àkọ́bí Iṣmaeli: Kedari, Adbeeli, Mibsamu, [30] Miṣima, Duma, Massa, Hadadi, Tema, [31] Jeturi, Nafiṣi, àti Kedema. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Iṣmaeli. [32] Àwọn ọmọ Ketura, obìnrin Abrahamu: Simrani, Jokṣani Medani, Midiani Iṣbaki àti Ṣua. Àwọn ọmọ Jokṣani: Ṣeba àti Dedani. [33] Àwọn ọmọ Midiani: Efani, Eferi, Hanoku, Abida àti Eldaa. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ìran Ketura. [34] Abrahamu sì jẹ́ baba Isaaki. Àwọn ọmọ Isaaki: Esau àti Israẹli. [35] Àwọn ọmọ Esau: Elifasi, Reueli, Jeuṣi, Jalamu, àti Kora. [36] Àwọn ọmọ Elifasi: Temani, Omari, Sefi, Gatamu àti Kenasi; láti Timna: Amaleki. [37] Àwọn ọmọ Reueli: Nahati, Sera, Ṣamma àti Missa. [38] Àwọn ọmọ Seiri: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana, Diṣoni, Eseri àti Diṣani. [39] Àwọn ọmọ Lotani: Hori àti Homamu: Timna sì ni arábìnrin Lotani. [40] Àwọn ọmọ Ṣobali: Afiani, Manahati, Ebali, Ṣefo àti Onamu. Àwọn ọmọ Sibeoni: Aiah àti Ana. [41] Àwọn ọmọ Ana: Diṣoni. Àwọn ọmọ Diṣoni: Hemdani, Eṣbani, Itrani, àti Kerani. [42] Àwọn ọmọ Eseri: Bilhani, Saafani àti Akani. Àwọn ọmọ Diṣani: Usi àti Arani. [43] Àwọn wọ̀nyí ni ọba tí ó jẹ ní Edomu, kí ó tó di pé ọba kankan jẹ lórí Israẹli: Bela ọmọ Beori, orúkọ ìlú rẹ̀ ni Dinhaba. [44] Nígbà tí Bela kú, Jobabu ọmọ Sera ti Bosra sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀. [45] Nígbà tí Jobabu kú, Huṣamu láti ilẹ̀ Temani sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀. [46] Nígbà tí Huṣamu kú, Hadadi ọmọ Bedadi tí ó kọlu Midiani ní ìgbẹ́ Moabu, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Afiti. [47] Nígbà tí Hadadi sì kú, Samla láti Masreka, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀. [48] Samla sì kú, Saulu ti Rehoboti létí odò sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀. [49] Nígbà tí Saulu kú, Baali-Hanani, ọmọ Akbori jẹ ọba ní ipò rẹ̀. [50] Nígbà tí Baali-Hanani kú, Hadadi ni ó jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Pau; orúkọ ìyàwó sì ni Mehetabeeli ọmọbìnrin Matiredi, ọmọbìnrin Mesahabu. [51] Hadadi sì kú pẹ̀lú. Àwọn baálẹ̀ Edomu ni: baálẹ̀ Timna, baálẹ̀ Alfa, baálẹ̀ Jeteti [52] baálẹ̀ Oholibama, baálẹ̀ Ela, baálẹ̀ Pinoni. [53] Baálẹ̀ Kenasi, baálẹ̀ Temani, baálẹ̀ Mibsari, [54] Magdieli àti Iramu. Àwọn wọ̀nyí ni baálẹ̀ Edomu.
