1 Kronika 8:1-40 OYCB
[1] Benjamini jẹ́ baba: Bela àkọ́bí rẹ̀, Aṣbeli ọmọkùnrin ni ẹ̀ẹ̀kejì, Ahara ẹ̀ẹ̀kẹ́ta, [2] Noha ẹ̀ẹ̀kẹrin àti Rafa ẹ̀karùnún. [3] Àwọn ọmọ Bela ni, Adari, Gera, Abihudi, [4] Abiṣua, Naamani, Ahoa, [5] Gera, Ṣefufani àti Huramu. [6] Wọ̀nyí ni àwọn ìran ọmọ Ehudu, tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé tí ó ń gbé ní Geba tí a sì lé kúrò lọ sí Manahati: [7] Naamani Ahijah àti Gera, tí ó lé wọn kúrò ní ìlú, àti tí ó sì jẹ́ baba Ussa àti Ahihudu. [8] A bí àwọn ọmọkùnrin fún Ṣaharaimu ní Moabu lẹ́yìn tí ó ti kọ àwọn ìyàwó rẹ̀ sílẹ̀, Huṣimu àti Baara. [9] Nípasẹ̀ ìyàwó rẹ̀ Hodeṣi ó ní Jobabu Sibia, Meṣa, Malkamu, [10] Jeusi, Sakia àti Mirma. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, olórí àwọn ìdílé. [11] Nípasẹ̀ Huṣimu ó ní Abitubu àti Elipali. [12] Àwọn ọmọ Elipali: Eberi, Miṣamu, Ṣemedu (ẹni tí ó kọ́ Ono àti Lodi pẹ̀lú àwọn ìletò àyíká rẹ̀.) [13] Pẹ̀lú Beriah àti Ṣema, tí wọ́n jẹ́ olórí àwọn ìdílé ti àwọn tí ó ń gbé ní Aijaloni àti àwọn tí ó lé àwọn olùgbé Gati kúrò. [14] Ahio, Ṣasaki, Jeremoti, [15] Sebadiah, Aradi, Ederi [16] Mikaeli, Iṣifa àti Joha jẹ́ àwọn ọmọ Beriah. [17] Sebadiah, Meṣullamu, Hiski, Heberi [18] Iṣimerai, Isiliahi àti Jobabu jẹ́ àwọn ọmọ Elipali. [19] Jakimu, Sikri, Sabdi, [20] Elienai, Siletai, Elieli, [21] Adaiah, Beraiah àti Ṣimrati jẹ́ àwọn ọmọ, Ṣimei. [22] Iṣipani Eberi, Elieli, [23] Abdoni, Sikri, Hanani, [24] Hananiah, Elamu, Anitotijah, [25] Ifediah àti Penueli jẹ́ àwọn ọmọ Ṣasaki. [26] Ṣamṣerai, Ṣeharaiah, Ataliah [27] Jareṣiah, Elijah àti Sikri jẹ́ àwọn ọmọ Jerohamu. [28] Gbogbo àwọn wọ̀nyí jẹ́ olórí àwọn ìdílé, olóyè gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ lẹ́sẹẹsẹ nínú ìtàn ìran wọn, wọ́n sì ń gbé ní Jerusalẹmu. [29] Jeieli, baba Gibeoni ń gbé ní Gibeoni. Ìyàwó o rẹ̀ a má jẹ́ Maaka, [30] àkọ́bí rẹ̀ a sì máa jẹ́ Abdoni wọ̀nyí sì ń tẹ̀lé Suri, Kiṣi, Baali, Neri, Nadabu, [31] Gedori Ahio, Sekeri [32] pẹ̀lú Mikiloti, tí ó jẹ́ baba Ṣimea. Wọ́n ń gbé ní ẹ̀bá ìbátan wọn ní Jerusalẹmu. [33] Neri jẹ́ baba Kiṣi, Kiṣi baba Saulu àti Saulu baba Jonatani, Malikiṣua, Abinadabu àti Eṣi-Baali. [34] Ọmọ Jonatani: Meribu-Baali tí ó jẹ́ baba Mika. [35] Àwọn ọmọ Mika: Pitoni, Meleki, Tarea, àti Ahasi. [36] Ahasi jẹ́ baba a Jeheada, Jeheada jẹ́ baba a Alemeti, Asmafeti àti Simri, Simri sì jẹ́ baba Mosa. [37] Mosa jẹ́ baba Binea; Rafa sì jẹ́ ọmọ rẹ̀, Eleasa ọmọ rẹ̀ àti Aseli ọmọ rẹ̀. [38] Aseli ní ọmọ mẹ́fà pẹ̀lú wọ̀nyí ni orúkọ wọn: Asrikamu, Bokeru, Iṣmaeli, Ṣeariah, Obadiah àti Hanani. Gbogbo wọ̀nyí ni ọmọ Aseli. [39] Àwọn ọmọ arákùnrin rẹ̀ Eseki: Ulamu àkọ́bí rẹ̀, Jeuṣi ọmọkùnrin ẹ̀ẹ̀kejì àti Elifeleti ẹ̀ẹ̀kẹ́ta. [40] Àwọn ọmọ Ulamu jẹ́ ògboyà jagunjagun tí ó lè gbá orin mú. Wọ́n ní ọ̀pọ̀ ọmọkùnrin àti ọmọ ọmọkùnrin áàdọ́jọ ní gbogbo rẹ̀. Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn ìdílé ìran ọmọ Benjamini.
